Pàdé Olùkọ́ni Ìlera Kídnì tó wà lẹ́yìn iṣẹ́ yìí
(Ìwádìí PhD, Ìlera Kídnì, Àwọn Awakọ̀ Tí ń Ṣiṣẹ́)
Rachel Bolanle jẹ́ nọọsi tí ó mọ̀ọ́mọ̀ọ́ nípa iṣẹ́ rẹ̀ gan-an, tí ó sì ní ọ̀pọ̀ amọ̀ja tó yàtọ̀. Ó ti kọ́ ara rẹ̀ dáadáa nípa iṣẹ́ nọọsi lórí ọ̀pọ̀ ọ̀nà.
Ó jẹ́ Nọọsi Tó Forúkọsílẹ̀ tí wọ́n kọ́ ní School of Nursing Akure ní Ondo State; ó tún jẹ́ Nọọsi Abiyamọ tí wọ́n kọ́ ní School of Midwifery Ilorin ní Kwara State; Nọọsi Ọmọde tí wọ́n kọ́ ní Post Basic Nursing UITH Ilorin; àti Nọọsi itoju kindirin tí wọ́n tún kọ́ ní UITH Ilorin náà.
Kò pé ní bẹ̀, ó tún lọ sí orílẹ̀-èdè Gẹ̀ẹ́sì láti túbọ̀ gòkè ní imọ̀ nípa ìtọju kidirin ní Sheffield Kidney Institute, Northern General Hospital ní Sheffield. Nípa ẹ̀kọ́ ilé-ẹ̀kọ́ gíga, Rachel ní B.Sc. Nursing láti KAAF University College ní Ghana, ó sì ní M.Sc. Nursing láti Lincoln University College ní Malaysia.
Ní báyìí, Rachel ni Deputy Director of Nursing ní University of Ilorin Teaching Hospital. Níbi yìí, ó ń darí iṣẹ́, ó ń tọ́jú ìdàgbàsókè àwọn oṣiṣẹ́ àti akẹ́kọ̀ọ́, ó sì ń dáàbò bo pé ìtọju aláìsàn wà ní ipele tó ga.
Ó tún ń ṣe ìwádìí PhD ní Bowen University ní Ìwó, níbi tí ó ti ń ṣe iṣẹ́ iwádìí pàtàkì kan tí wọ́n pè ní:
Àbájáde Ìtọju Onígbàsókè Tí Nọọsi Darí lórí Ìmọ̀, Ìhùwàsí àti Ìṣe àwọn Nnkan tí ń fa Àrùn Kidirin Alákànṣe lárà Awakọ Ọkọ̀ ero ní díẹ̀ lára Ọgbà Iwakọ ní Gúúsù Ìwọ̀ Oòrùn Nàìjíríà
Ìwádìí rẹ̀ ń bójú tó ìṣòro ilera gbogbogbò tó ṣe pàtàkì. Àrùn Kidirin Alákànṣe jẹ́ ọ̀kan nínú àwọn àìlera tó ń pa ènìyàn jù lọ ní ayé, ṣùgbọ́n ọ̀pọ̀ ènìyàn ò mọ̀ nígbà tí ó bá ń gbòòrò síi títí tí yóò fi lewu gan. Ní Nàìjíríà, ó ń pọ̀ sí i lójoojúmọ́, wọ́n sì ń sọ pé ní ọdún 2040, yóò wà ní àkójọ àrùn marun-un tó ń fa ikú jù lọ ní agbáyé.
Nígbà tí Rachel rí i pé àwọn awakọ ọkọ̀ ero ní ewu gan-an torí ìlànà ìgbésí ayé wọn, ó ṣe àfihàn pé ó yẹ kí a fọwọ́sowọpọ̀ pẹ̀lú wọn. Ní bẹ̀, ó fi ìwádìí rẹ̀ ṣe káàkiri ọgbà iwakọ mejila ní Oyo, Ekiti àti Osun. Ó ń lo eto ìmọ̀ orí ayélujára tí nọọsi darí, tí wọ́n ṣe ní Gẹ̀ẹ́sì, Yorùbá àti Pidgin, láti kọ́ wọn nípa àrùn náà, kí ó ṣe àtúnṣe àwọn ihuwasi tó lewu, kí wọ́n sì lè gbé ìgbésí ayé tó dára ju bẹ́ẹ̀ lọ.
Nípasẹ̀ gbogbo iṣẹ́ yìí, ohun tí Rachel fẹ́ ni kí a lè ní ọ̀nà tí yóò ṣiṣẹ́ lọ́ọ́jọ́ pípẹ́ láti dín àrùn kidirin alákànṣe kù, kí ó sì léwu kere fún àwọn awakọ, tó jẹ́ ọ̀kan nínú àwọn ẹgbẹ́ tó ní ewu jù lọ ní orílẹ̀-èdè Nàìjíríà.